Ìròyìn asọ̀tàn
Ìròyìn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde
Súyà Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà!
Mọ́là kan ni a rí níbí tí ó jókòó sídìí Àtẹ Súyà rẹ̀ Súyà (tí wọ́n ń pè é báyìí pé Sú-yá-à) Ìyẹn ni orúkọ ìjànjá-ẹran kan tí a ń yan lórí ayanran tó fẹjú, pẹ̀lú òróró, àlùbọ́sà àti iyọ̀. Súyà jẹ́ gbajúgbajà ohun jíjẹ láàárín àwọn ọlọ́rọ̀ àti bọ̀rọ̀kìní...
Ọlọ́pàá Orílẹ̀-èdè Indonesia mú akẹ́kọ̀ọ́ mẹ́fà tí ó na àsíá ‘Àyájọ́ òmìnira orílẹ̀-èdè Papua’ tí a gbẹ́sẹ̀lé sókè
Ọjọ́ kìnínní, oṣù Kejìlá, ọdún 2021 ni àwọn ènìyán kà sí Ọjọ́ Òmìnira orílẹ̀-èdè Ìwọ̀ Oòrùn Papua, sàmì àyájọ́ ọgọ́ta ọdún tí a kọ́kọ́ ta àsíá Ìràwọ̀ Òwúrọ̀ ní ìgbésẹ̀ láti gba òmìnira lọ́wọ́ ìjọba àmúnisìn Dutch
Boji rè é, Ajá tí ó máa ń jayé orí i rẹ̀ kiri ìgboro Istanbul nínú ọkọ̀ èrò
Ẹ pàdé Boji, Ajá kan ni Istanbul tí ó máa ń wọ ọkọ̀ èrò kiri ìgboro lójoojúmọ́.
Rising Voices’ Activismo Lenguas gba Àmì-ẹ̀yẹ Èdè Abínibí Àgbáyé
"Àmì-ẹ̀yẹ yìí dúró gẹ́gẹ́ bí ipa tí àwọn ajìjàngbara èdè lórí ẹ̀rọ-ayárabíàṣá ń ní jákèjádò agbègbè Latin Amẹ́ríkà àti arapa ribiribi iṣẹ́ wọn."
Àwọn ìdílé l’órílẹ̀-èdè Kenya fi ara kááṣá látàrí ipa ìfọjọ́-kún ilé-ìwé tí ó wà ní títì pa
Látàrí títì pa àwọn ilé-ìwé ní orílẹ̀-èdè Kenya, àìdọgba ti kọjá bẹ́ẹ̀. Àwọn amòye nídìí ètò-ẹ̀kọ́ fẹ́ kí ìjọba tún iná ètò-ẹ̀kọ́ dá látì lè jẹ́ kí ìkẹ́kọ̀ọ́ ó kárí tẹrútọmọ
Ní orílẹ̀-èdè Turkey, ẹgbẹẹgbẹ̀rún méjì àbọ̀ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ni wọ́n jókòó ṣe ìdánwò ìgbaniwọlẹ́ sí Ifásitì
Awuyewuye wà lórí ìdáwò ọdún yìí -- kò sì kín ṣe látàri àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19.
Ní àwọn ìlú tí ó wà lábẹ́ ìṣàkóso Assad ní ilẹ̀ Syria, àwọn alákòóso sọ báyìí pé ‘kò sí èni tí ó ní àrùn kòrónà’
Láti tẹnpẹlẹ mọ́ ìṣàkóso, sáà Assad ṣe ohun gbogbo tí ó lè ṣe ní ti ìkọ̀jálẹ̀ wí pé kò sí COVID-19 ní àwọn agbègbè tí ó wà lábẹ̀ ìṣàkóso rẹ̀.
Àwọn obìnrin ní Nàìjíríà kojú àdó-olóró àgbẹ́sẹ̀léró àgbàwí ọ̀rọ̀ ìṣèlú lórí ẹ̀rọ-ayélujára
Fakhriyyah Hashim, ọ̀kan lára àwọn olùdásílẹ̀ ìpolongo #ArewaMeToo ní àríwá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà sọ wí pé “Mo ti kọ́ ìfaradà.”
Ní Burundi, àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin tí a fi sátìmọ́lé ń dúró de ìpinnu ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn
A fi ẹ̀sùn ìlọ́wọ́sí ìdúkokò mọ́ ààbò ìlú ni a fi kan àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin náà látàrí iṣẹ́-ìjẹ́ ẹ̀fẹ̀ lásán tí wọ́n fi ṣọwọ́ nígbà tí wọ́n kó ròyìn ẹgbẹ́ ọlọ́tẹ̀ kan jọ.
Túwíìtì nípa èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ àti ẹ̀tọ́ sí ìlò ẹ̀rọ ayárabíàṣá
Rising Voices ń kọ́mọlùbọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn akẹgbẹ́ẹ wa ní yàrá ìròyìn Ohùn Àgbáyé Agbègbè Sahara Ilẹ̀-Adúláwọ̀ fún ìpolongo tuntun lórí ẹ̀rọ alátagbà láti ṣe àyẹ̀wò ìbáṣepọ̀ tí ó ń bẹ láàárín àwọn èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ àti ẹ̀tọ́ sí ẹ̀rọ ayárabíàṣá.