Ìròyìn asọ̀tàn nípa Ètò ìjọba
Ìròyìn nípa Ètò ìjọba
Àwọn ìdílé l’órílẹ̀-èdè Kenya fi ara kááṣá látàrí ipa ìfọjọ́-kún ilé-ìwé tí ó wà ní títì pa
Látàrí títì pa àwọn ilé-ìwé ní orílẹ̀-èdè Kenya, àìdọgba ti kọjá bẹ́ẹ̀. Àwọn amòye nídìí ètò-ẹ̀kọ́ fẹ́ kí ìjọba tún iná ètò-ẹ̀kọ́ dá látì lè jẹ́ kí ìkẹ́kọ̀ọ́ ó kárí tẹrútọmọ
Ní àwọn ìlú tí ó wà lábẹ́ ìṣàkóso Assad ní ilẹ̀ Syria, àwọn alákòóso sọ báyìí pé ‘kò sí èni tí ó ní àrùn kòrónà’
Láti tẹnpẹlẹ mọ́ ìṣàkóso, sáà Assad ṣe ohun gbogbo tí ó lè ṣe ní ti ìkọ̀jálẹ̀ wí pé kò sí COVID-19 ní àwọn agbègbè tí ó wà lábẹ̀ ìṣàkóso rẹ̀.
Ní Burundi, àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin tí a fi sátìmọ́lé ń dúró de ìpinnu ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn
A fi ẹ̀sùn ìlọ́wọ́sí ìdúkokò mọ́ ààbò ìlú ni a fi kan àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin náà látàrí iṣẹ́-ìjẹ́ ẹ̀fẹ̀ lásán tí wọ́n fi ṣọwọ́ nígbà tí wọ́n kó ròyìn ẹgbẹ́ ọlọ́tẹ̀ kan jọ.
COVID-19 ṣe àgbéǹde ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tó burú jáì nípa ìdánwò egbògi ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀
Ilẹ̀-Adúláwọ̀ 'kì í ṣe yàrá ìṣàyẹ̀wò' fún egbògi àjẹsára COVID-19. Àríyànjiyàn tí ó dá lóríi ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tí ó burú jáì nípa fífi ọmọ ènìyàn ṣe ìdánwò àti fífọwọ́ọlá gbá ọmọ Ilẹ̀-Adúláwọ̀ lójú.
Ìgbàgbọ́ ọba kan nínú ewé àtegbó fún ìwòsàn COVID-19 f'ara gbún ìmọ̀-ìjìnlẹ̀ l'órílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Ọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yìí nígbàgbọ́ nínú ewé àtegbó fún àwòtán COVID-19. Àmọ́ fífi Ògún gbárí láìfẹ̀rìílàdìí lórí Twitter fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbárìn lè ṣini lọ́kàn — ó sì léwu — fún àwọn ènìyàn.
Àwọn Iléèjọsìn ní Greece àti Àríwá Macedonia kọ̀ láti yí ọwọ́ àwọn ìlànà-ìsìn wọn padà k'ó ba má fàyè gba àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19 t'ó ń ràn ká
Ìlànà ìsìn tí a mọ̀ sí Jíjẹara àti mímu ẹ̀jẹ̀ Olúwa tàbí Oúnjẹ Ìkẹyìn ní èyí tí àwọn ọmọ lẹ́yìn Krístì tí ó ń tẹ̀lé ìlànà ìsìn àtijọ́ yóò máa pín wáìnì tí a ti sọ di mímọ́ mu pẹ̀lú ṣíbí kan náà, àwọn Ìjọ Àgùdàá máa ń jẹ ẹ̀bẹ àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí wọ́n fi ẹnu gbà lọ́wọ́ àlùfáà.
Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ ní Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn akẹgbẹ́-ẹ wọn láti sààmì ayẹyẹ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ọdún-un 2020
Àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀-ọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ orí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lágbàáyé láti sààmì Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé lọ́jọ́ 13 oṣù Èrèlé ọdún-un 2020 àti láti fọn rere iṣẹ́ ìdàgbàsókè àgbà-ńlá ayé tí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ń ṣe.
Kíni ìdí irẹ̀ tí Donald Trump ṣe l'ókìkí ní Nàìjíríà?
Ratings for US President Donald Trump’s handling of world affairs are largely negative around the world. But not in Nigeria.
Ilé ẹjọ́ gíga Tanzania pa á láṣẹ fún ìfòpinsí ìsoyìgì láàárín àgbàlagbà àti ọmọdé láì wo ti ìgbésẹ̀ ìmúpadàa rẹ̀
Nínú oṣù Ọ̀wàrà 2019, Ilé-ẹjọ́ Gíga Tanzania ṣe ìdímú ṣinṣin ìdájọ́ láti fòpin sí ìgbéyàwó ọmọdé. Ìdájọ́ ilé ẹjọ́ náà jẹ́ atọ́ka sí ìfòpinsí àwọn àṣà tí ó ń mú ìpalára bá àwọn ọmọdébìnrin àti onírúurú ẹlẹ́yàmẹyà tòun ìfọwọ́rọ́sẹ́yìn àwọn ọmọdébìnrin.
Ìrọ́lù ọlọ́pàá tí í mú ikú bá ‘ni ní Guinea bí Ààrẹ Alpha Condé ṣe kọ̀ láì gbé’ jọba sílẹ̀
Ìwà ipá ọlọ́pàá tí ó ń ṣekú pani ní Guinea bí ààrẹ ṣe gbèrò láti yí ìwé-òfin padà kí ó bá wà lórí ipò. Àwọn afẹ̀hónúhàn pa ẹni mẹ́fà àti ọlọ́pàá kan, ọ̀pọ́ sì fara pa.