Ìròyìn asọ̀tàn nípa Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn
Ìròyìn nípa Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn
Fún Ayẹyẹ Àìsùn Ọdún Tuntun àwọn Ilé-Ìwé ní Moscow, àwọn orin kan ò bójúmu
Ní àpapọ̀, àtòjọ náà ní àwọn olórin àti ẹgbẹ́ eléré 29. Díẹ̀ nínú wọn, bíi Little Big àti Manizha, ti ṣojú orílẹ̀-èdè Russia rí ní ìdíje Eurovision fún ọdún púpọ̀ látẹ̀yìnwá. Gbogbo wọn pata ni wọ́n bu ẹnu àtẹ́ lu ìkọlù orílẹ̀-èdè Russia sí Ukraine ní gbangba
Àwọn àjòjì tí wọ́n gba òmìnira sọ ìrírí wọn ní ọgbà ẹ̀wọ̀n Myanmar
"Mà á fẹ́ láti ṣàtẹnumọ́ pé àwọn tí kò nífọ̀n-léèékánná lọ̀pọ̀ àwọn olùfaragbá ìyà àwọn ológun, èyí tí ó sì ń tẹ̀síwajú."
Ọlọ́pàá Orílẹ̀-èdè Indonesia mú akẹ́kọ̀ọ́ mẹ́fà tí ó na àsíá ‘Àyájọ́ òmìnira orílẹ̀-èdè Papua’ tí a gbẹ́sẹ̀lé sókè
Ọjọ́ kìnínní, oṣù Kejìlá, ọdún 2021 ni àwọn ènìyán kà sí Ọjọ́ Òmìnira orílẹ̀-èdè Ìwọ̀ Oòrùn Papua, sàmì àyájọ́ ọgọ́ta ọdún tí a kọ́kọ́ ta àsíá Ìràwọ̀ Òwúrọ̀ ní ìgbésẹ̀ láti gba òmìnira lọ́wọ́ ìjọba àmúnisìn Dutch
Ìlàkàkà láti fi òpin sí òkúrorò SARS ẹ̀ka ilé-isẹ́ ọlọ́pàá ilẹ̀ Nàìjííríà ń tẹ̀síwájú.
Ìbéèrè lórí ẹni tí ó ń darí àwọn Ọlọ́pàá àti ikọ̀ SARS kò tíì fi gbogbo ara rí ìdáhùn. Ìwé-òfin ilẹ̀ náà gbágbára ìdárí lé ààrẹ lọ́wọ́, ó sì gbé agbára àmójútó lé Ọ̀gá àgbà ilé iṣẹ́ Ọlọ́pàá lọ́wọ́.
‘Boca de Rua': Ìwé ìròyìn ilẹ̀ brazil láti ọwọ́ àwọn ènìyàn tí ó ń gbé ní ojú òpópónà
Wọ́n dá a sílẹ̀ ní nǹkan bi 20 ọdún sẹ́yìn. ‘Boca de Rua’ nìkan ni ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Àwọn Ìwé Ìròyìn Ẹsẹ̀kùkú Àgbáyé tí àwọn ẹni tí ó ń sun ojú títì ń ṣe jáde.
Ní àwọn ìlú tí ó wà lábẹ́ ìṣàkóso Assad ní ilẹ̀ Syria, àwọn alákòóso sọ báyìí pé ‘kò sí èni tí ó ní àrùn kòrónà’
Láti tẹnpẹlẹ mọ́ ìṣàkóso, sáà Assad ṣe ohun gbogbo tí ó lè ṣe ní ti ìkọ̀jálẹ̀ wí pé kò sí COVID-19 ní àwọn agbègbè tí ó wà lábẹ̀ ìṣàkóso rẹ̀.
Àwọn obìnrin ní Nàìjíríà kojú àdó-olóró àgbẹ́sẹ̀léró àgbàwí ọ̀rọ̀ ìṣèlú lórí ẹ̀rọ-ayélujára
Fakhriyyah Hashim, ọ̀kan lára àwọn olùdásílẹ̀ ìpolongo #ArewaMeToo ní àríwá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà sọ wí pé “Mo ti kọ́ ìfaradà.”
Ní Burundi, àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin tí a fi sátìmọ́lé ń dúró de ìpinnu ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn
A fi ẹ̀sùn ìlọ́wọ́sí ìdúkokò mọ́ ààbò ìlú ni a fi kan àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin náà látàrí iṣẹ́-ìjẹ́ ẹ̀fẹ̀ lásán tí wọ́n fi ṣọwọ́ nígbà tí wọ́n kó ròyìn ẹgbẹ́ ọlọ́tẹ̀ kan jọ.
COVID-19 ṣe àgbéǹde ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tó burú jáì nípa ìdánwò egbògi ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀
Ilẹ̀-Adúláwọ̀ 'kì í ṣe yàrá ìṣàyẹ̀wò' fún egbògi àjẹsára COVID-19. Àríyànjiyàn tí ó dá lóríi ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tí ó burú jáì nípa fífi ọmọ ènìyàn ṣe ìdánwò àti fífọwọ́ọlá gbá ọmọ Ilẹ̀-Adúláwọ̀ lójú.
Àwọn òṣìṣẹ́ iléeṣẹ́ aṣẹ̀wùtà orílẹ̀-èdè Cambodia daṣẹ́sílẹ̀ látàrí àìsan owó ọ̀yà wọn lásìkò àjàkálẹ̀ COVID-19
"A kò leè jẹ́ k'áwọn agbanisíṣẹ́ ó wí àwáwí tí yóò f'àfàsẹ́yìn fówó ọ̀yà àwọn òṣìṣẹ́, nítorí àwọn òṣìṣẹ́ ti jẹ gbèsè, wọn kò sì gbọdọ̀ jáfara láti san owó wọn."