Ìròyìn asọ̀tàn nípa Àṣà àti Iṣẹ́-ọnà
Ìròyìn nípa Àṣà àti Iṣẹ́-ọnà
Olórin Calypso Trinidad àti Tobago, Black Stalin, àwòkọ́ṣe ‘ọkùnrin Caribbean,’ jáde láyé ní ẹni Ọdún 81
Ògbó aládàánìkàn ronú tó gbóná àti olùpilẹ̀sẹ̀ ọ̀rọ̀ orin, ní gbogbo ìlàkàkà rẹ Stalin gbìyànjú láti jẹ́ kí ohun gbogbo lọ déédé.
Orin ẹ̀hónú: àwọn ọ̀dọ́mọdé òǹkọrin ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ń kọrin tako ìwà ìrẹ́jẹ láwùjọ
Àwọn ọ̀dọ́mọdé olórin orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti tẹ̀síwájú nínú àṣà kíkọ orin tako ìrẹ́jẹ láwùjọ. Èhónú #EndSARS ṣe ìtanijí ọkàn wọn sí ìkópa nínú ètò òṣèlú, eléyìí tí ó ti ń wòòkùn.
Fún Ayẹyẹ Àìsùn Ọdún Tuntun àwọn Ilé-Ìwé ní Moscow, àwọn orin kan ò bójúmu
Ní àpapọ̀, àtòjọ náà ní àwọn olórin àti ẹgbẹ́ eléré 29. Díẹ̀ nínú wọn, bíi Little Big àti Manizha, ti ṣojú orílẹ̀-èdè Russia rí ní ìdíje Eurovision fún ọdún púpọ̀ látẹ̀yìnwá. Gbogbo wọn pata ni wọ́n bu ẹnu àtẹ́ lu ìkọlù orílẹ̀-èdè Russia sí Ukraine ní gbangba
Àwọn ìdílé l’órílẹ̀-èdè Kenya fi ara kááṣá látàrí ipa ìfọjọ́-kún ilé-ìwé tí ó wà ní títì pa
Látàrí títì pa àwọn ilé-ìwé ní orílẹ̀-èdè Kenya, àìdọgba ti kọjá bẹ́ẹ̀. Àwọn amòye nídìí ètò-ẹ̀kọ́ fẹ́ kí ìjọba tún iná ètò-ẹ̀kọ́ dá látì lè jẹ́ kí ìkẹ́kọ̀ọ́ ó kárí tẹrútọmọ
Ní orílẹ̀-èdè Turkey, ẹgbẹẹgbẹ̀rún méjì àbọ̀ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ni wọ́n jókòó ṣe ìdánwò ìgbaniwọlẹ́ sí Ifásitì
Awuyewuye wà lórí ìdáwò ọdún yìí -- kò sì kín ṣe látàri àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19.
Ìgbàgbọ́ ọba kan nínú ewé àtegbó fún ìwòsàn COVID-19 f'ara gbún ìmọ̀-ìjìnlẹ̀ l'órílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Ọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yìí nígbàgbọ́ nínú ewé àtegbó fún àwòtán COVID-19. Àmọ́ fífi Ògún gbárí láìfẹ̀rìílàdìí lórí Twitter fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbárìn lè ṣini lọ́kàn — ó sì léwu — fún àwọn ènìyàn.
Ọ̀rọ̀ àyálò nínú èdè Yorùbá: Bí èdè ṣe yí padà
Lílo àwọn ojúlówó ọ̀rọ̀ èdè Yorùbá pọ́nbélé máa ń mú kí àṣà — ó gbòòrò — tí yóò sí máa gbilẹ̀.
Olóyè yìí nírètí wí pé àwọn ọmọ Yorùbá yóò tẹ́wọ́ gba ‘alífábẹ́ẹ̀tì t'ó ń sọ̀rọ̀’ tí òun hu ìmọ̀ rẹ̀
Kíkọ Yorùbá nílànà Látíìnì yóò di àfìẹ́yìn láì pẹ́ nítorí ọmọ káàárọ̀-o-ò-jí-ire kan, Olóyè Tolúlàṣẹ Ògúntósìn, ti hùmọ̀ ìlànà ìṣọwọ́kọ tuntun fún kíkọ èdè Yorùbá
Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ ní Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn akẹgbẹ́-ẹ wọn láti sààmì ayẹyẹ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ọdún-un 2020
Àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀-ọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ orí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lágbàáyé láti sààmì Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé lọ́jọ́ 13 oṣù Èrèlé ọdún-un 2020 àti láti fọn rere iṣẹ́ ìdàgbàsókè àgbà-ńlá ayé tí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ń ṣe.
Ilẹ̀-Adúláwọ̀ rí àbọ̀ ẹgbẹẹgbẹ̀rún-lọ́nà-ẹgbẹ̀rún owóo dollar láti ọ̀dọ̀ Ilé-ìfowópamọ́sí ńláńlá fún ìgbéfúkẹ́ Iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá
“Nítorí àìtó ìdókoòwò ń'nú iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá àti àṣà, Ilẹ̀-Adúláwọ̀ kò sí ń'nú ọjà iṣẹ́ ọpọlọ, àti ìdáraáwò ní àgbáyé," Benedict Oramah, ààrẹ Afreximbank ló sọ bẹ́ẹ̀.