Ìròyìn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde
Àwọn obìnrin ní Nàìjíríà kojú àdó-olóró àgbẹ́sẹ̀léró àgbàwí ọ̀rọ̀ ìṣèlú lórí ẹ̀rọ-ayélujára
Fakhriyyah Hashim, ọ̀kan lára àwọn olùdásílẹ̀ ìpolongo #ArewaMeToo ní àríwá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà sọ wí pé “Mo ti kọ́ ìfaradà.”
Ní Burundi, àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin tí a fi sátìmọ́lé ń dúró de ìpinnu ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn
A fi ẹ̀sùn ìlọ́wọ́sí ìdúkokò mọ́ ààbò ìlú ni a fi kan àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin náà látàrí iṣẹ́-ìjẹ́ ẹ̀fẹ̀ lásán tí wọ́n fi ṣọwọ́ nígbà tí wọ́n kó ròyìn ẹgbẹ́ ọlọ́tẹ̀ kan jọ.
Túwíìtì nípa èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ àti ẹ̀tọ́ sí ìlò ẹ̀rọ ayárabíàṣá
Rising Voices ń kọ́mọlùbọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn akẹgbẹ́ẹ wa ní yàrá ìròyìn Ohùn Àgbáyé Agbègbè Sahara Ilẹ̀-Adúláwọ̀ fún ìpolongo tuntun lórí ẹ̀rọ alátagbà láti ṣe àyẹ̀wò ìbáṣepọ̀ tí ó ń bẹ láàárín àwọn èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ àti ẹ̀tọ́ sí ẹ̀rọ ayárabíàṣá.
COVID-19 ṣe àgbéǹde ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tó burú jáì nípa ìdánwò egbògi ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀
Ilẹ̀-Adúláwọ̀ 'kì í ṣe yàrá ìṣàyẹ̀wò' fún egbògi àjẹsára COVID-19. Àríyànjiyàn tí ó dá lóríi ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tí ó burú jáì nípa fífi ọmọ ènìyàn ṣe ìdánwò àti fífọwọ́ọlá gbá ọmọ Ilẹ̀-Adúláwọ̀ lójú.
Àwọn Ilé Iṣẹ́ ẹ̀rọ-ìbánisọ̀rọ̀ ní Mozambique àti Cape Verde tẹ́ pẹpẹ ètò ẹ̀dínwó fún ayélujára lórí ẹ̀rọ alágbèéká láti mú kí àwọn ọmọ-ìlú ó dúró sílé
Àwọn tó ń lẹ̀rọ-ìbánisọ̀rọ̀ alágbèéká ní Cape Verde yóò jẹ àǹfààní ọ̀fẹ́ MB 2 fún oṣù kan gbáko, lẹ́yìn tí àwọn ti Mozambique lè ra GB 5 ní 1.50 iye owó US.Cape Verdeans mobile users will have 2 MB of free data on the next 30 days, while Mozambicans could purchase up to 5 GB for 1.50 USD.Cape Verdeans mobile users will have 2 MB of free data on the next 30 days, while Mozambicans could purchase up to 5 GB for 1.50 USD.
Ọ̀nà wo ni àrùn COVID-19 ń gbà ṣe àtúnṣe sí ètò ìṣèlú àti ẹ̀yìn-ọ̀la Orílẹ̀-èdè China lágbàáyé?
Àrùn kòkòrò àìfojúrí kòrónà Wuhan náà kì í ṣe ìkọlù ètò ìlera lásán, ó jẹ́ àkókò òtítọ́ ètò ìṣèlú tí ó lákaakì.
Orílẹ̀-Èdè Nàìjíríà fi òfin de ìrìn-àjò lójúnà ìṣàmójútó àwọn tó ti kó kòkòrò àìfojúrí COVID 19
Àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lórí ayélujára béèrè fún ìfòfindè arìnrìnàjò láti orílẹ̀-èdè tí COVID-19 ti gbilẹ̀. Èyí á ró ojúṣẹ́ orílẹ̀-èdè sí ìtànkálẹ̀ yìí lágbára.
Ìgbàgbọ́ ọba kan nínú ewé àtegbó fún ìwòsàn COVID-19 f'ara gbún ìmọ̀-ìjìnlẹ̀ l'órílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Ọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yìí nígbàgbọ́ nínú ewé àtegbó fún àwòtán COVID-19. Àmọ́ fífi Ògún gbárí láìfẹ̀rìílàdìí lórí Twitter fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbárìn lè ṣini lọ́kàn — ó sì léwu — fún àwọn ènìyàn.
Àwọn òṣìṣẹ́ iléeṣẹ́ aṣẹ̀wùtà orílẹ̀-èdè Cambodia daṣẹ́sílẹ̀ látàrí àìsan owó ọ̀yà wọn lásìkò àjàkálẹ̀ COVID-19
"A kò leè jẹ́ k'áwọn agbanisíṣẹ́ ó wí àwáwí tí yóò f'àfàsẹ́yìn fówó ọ̀yà àwọn òṣìṣẹ́, nítorí àwọn òṣìṣẹ́ ti jẹ gbèsè, wọn kò sì gbọdọ̀ jáfara láti san owó wọn."
Àwọn Iléèjọsìn ní Greece àti Àríwá Macedonia kọ̀ láti yí ọwọ́ àwọn ìlànà-ìsìn wọn padà k'ó ba má fàyè gba àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19 t'ó ń ràn ká
Ìlànà ìsìn tí a mọ̀ sí Jíjẹara àti mímu ẹ̀jẹ̀ Olúwa tàbí Oúnjẹ Ìkẹyìn ní èyí tí àwọn ọmọ lẹ́yìn Krístì tí ó ń tẹ̀lé ìlànà ìsìn àtijọ́ yóò máa pín wáìnì tí a ti sọ di mímọ́ mu pẹ̀lú ṣíbí kan náà, àwọn Ìjọ Àgùdàá máa ń jẹ ẹ̀bẹ àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí wọ́n fi ẹnu gbà lọ́wọ́ àlùfáà.