Ìròyìn nípa Caribbean
Ààmì ìdánimọ̀ orílẹ̀ èdèe Jamaica tí Kanye West lò di awuyewuye tí ó dá fìrìgbagbòó lórí ‘ìsààmì’
"Ìṣàkóso ìjọba tó lọ kò rí ọrọ̀ tó wà nínú àwọn ààmìi orílẹ̀ èdèe ‘Jamaica’ tàbí èyí [tó dúró fún] orílẹ̀ èdè bíi àsíá ìlú àti ti ológun..."
Iyùn Tobago tí ó ti ń pàwọ̀dà fi hàn gbàgàdàgbagada pé kò sí ọ̀nà mìíràn ju kíkojú àyípadà ojú-ọjọ́
Ìgbóná òkun ń kóbá àwọn òkúta iyùn-un Tobago àti àwọn erékùṣù Ọ̀sàa Caribbean, a bá onímọ̀ ìṣẹ̀dá kan tí ọjọ́ iwájúu wọn jẹ́ lógún sọ̀rọ̀.
Àyájọ́ Ọjọ́ Òmìnira ní Trinidad àti Tobago — àmọ́ ǹjẹ́ orílẹ̀-èdè náà ní òmìnira bí?
"Òmìnira yìí faramọ́ ẹni tí o jẹ́, ibi tí o ti ṣẹ̀ wá, ẹ̀jẹ̀ àti ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìwá tí ó wà nínú iṣan-ẹ̀jẹ̀ rẹ"
‘Ohùn-un Jamaica fún Àyípadà Ojú-ọjọ́’ fi orin jíṣẹ́ẹ wọn
Iléeṣẹ́ tí kì í ṣe ti ìjọba ń ṣe ìgbélárugẹ àwọn ọ̀nà tí a lè gba jẹ́ iṣẹ́ yìí nípa lílo iṣẹ́ ọpọlọ orin láti kéde nípa àyípadà ojú-ọjọ́.
Ta ni yóò jáwé olúborí nínú Ayẹyẹ ijó ìta-gbangba orílẹ̀-èdè Trinidad àti Tobago ọdún-un 2019?
Orin tí ó dùn ún gbọ́ létí, ègbè tí ó ṣòro láti gbàgbé ... jẹ́ díẹ̀ lára àwọn ohun idán tí ó mú orin Ijó ìta-gbangba Ìwọ́de Ojúnà Trinidad àti Tobago yàrà ọ̀tọ̀.
Ìjà láàárín ìràwọ̀ akọrin soca Trinidad àti Tobago jẹ́ àmì tí ó dára fún orin àtijọ́
ìforinjìjà tí kò dénú ni a ti rì bọ inú orin Calipso láti orísun, èyí kò yàtọ̀ nínú àdàlùu rẹ̀ tí í ṣe soca ìgbàlódé.