Ìròyìn asọ̀tàn nípa Nàìjíríà
Ìròyìn nípa Nàìjíríà
Bí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣe kojú ìdábẹ́ Ọmọbìnrin èyí tí ó ń ṣe lemọ́lemọ́: Ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pẹ̀lú Dókítà Chris Ugwu
Abẹ́dídá máa ń yọrí sí ìrora tó lágbára, ṣíṣe àgbákò àrùn àìfojú rí, ẹ̀jẹ̀ yíya lọ́pọ̀lọpọ̀, àìle kápá ojú ilé ìtọ̀, làásìgbò ní ìgbà ìbímọ, ìpayà, àti ní ìgbà mìíràn, ikú pàápàá. Ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, ẹkùn tí ìdábẹ́ fún ọmọbìnrin ti gbilẹ̀ jùlọ ni apá gúúsù-ìwọ̀ oòrùn àti gúúsù-ìlà oòrùn.
Àwọn Jàndùkú Èkó orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ń Dá Ìpayà bá àwọn aráàlú, ń lọ́ àwọn awakọ̀ èrò lọ́wọ́gbà, wọ́n sì ń ba nǹkan jẹ́
Àwọn ọmọ ìta (agbèrò) ń fayé ni àwọn olùgbé Èkó lára. Wọ́n ń gbowó lọ́wọ́ awakọ̀, ta egbòogi olóró, pàdíàpòpọ̀ pẹ̀lú àwọn olóṣèlú gẹ́gẹ́ bí jàgídíjàgan tí wọ́n sì ń dá ẹ̀mi légbodò pẹ̀lú àwọn ìjà wọn.
Súyà Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà!
Mọ́là kan ni a rí níbí tí ó jókòó sídìí Àtẹ Súyà rẹ̀ Súyà (tí wọ́n ń pè é báyìí pé Sú-yá-à) Ìyẹn ni orúkọ ìjànjá-ẹran kan tí a ń yan lórí ayanran tó fẹjú, pẹ̀lú òróró, àlùbọ́sà àti iyọ̀. Súyà jẹ́ gbajúgbajà ohun jíjẹ láàárín àwọn ọlọ́rọ̀ àti bọ̀rọ̀kìní...
Ìlàkàkà láti fi òpin sí òkúrorò SARS ẹ̀ka ilé-isẹ́ ọlọ́pàá ilẹ̀ Nàìjííríà ń tẹ̀síwájú.
Ìbéèrè lórí ẹni tí ó ń darí àwọn Ọlọ́pàá àti ikọ̀ SARS kò tíì fi gbogbo ara rí ìdáhùn. Ìwé-òfin ilẹ̀ náà gbágbára ìdárí lé ààrẹ lọ́wọ́, ó sì gbé agbára àmójútó lé Ọ̀gá àgbà ilé iṣẹ́ Ọlọ́pàá lọ́wọ́.
Àwọn obìnrin ní Nàìjíríà kojú àdó-olóró àgbẹ́sẹ̀léró àgbàwí ọ̀rọ̀ ìṣèlú lórí ẹ̀rọ-ayélujára
Fakhriyyah Hashim, ọ̀kan lára àwọn olùdásílẹ̀ ìpolongo #ArewaMeToo ní àríwá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà sọ wí pé “Mo ti kọ́ ìfaradà.”
COVID-19 ṣe àgbéǹde ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tó burú jáì nípa ìdánwò egbògi ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀
Ilẹ̀-Adúláwọ̀ 'kì í ṣe yàrá ìṣàyẹ̀wò' fún egbògi àjẹsára COVID-19. Àríyànjiyàn tí ó dá lóríi ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tí ó burú jáì nípa fífi ọmọ ènìyàn ṣe ìdánwò àti fífọwọ́ọlá gbá ọmọ Ilẹ̀-Adúláwọ̀ lójú.
Ìgbàgbọ́ ọba kan nínú ewé àtegbó fún ìwòsàn COVID-19 f'ara gbún ìmọ̀-ìjìnlẹ̀ l'órílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Ọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yìí nígbàgbọ́ nínú ewé àtegbó fún àwòtán COVID-19. Àmọ́ fífi Ògún gbárí láìfẹ̀rìílàdìí lórí Twitter fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbárìn lè ṣini lọ́kàn — ó sì léwu — fún àwọn ènìyàn.
Sísọnù sínú ògbufọ̀: Ìdí tí Atúmọ̀ Google ṣe ń kùnà — nínú títúmọ̀ èdè Yorùbá — àti àwọn èdè mìíràn
Bí àwọn iléeṣẹ́ onímọ̀ ẹ̀rọ ṣe ń gbìyànjú láti mú kí ògbufọ̀ èdè wà lárọ̀ọ́wọ́tó fún onírúurú èdè lórí ayélujára, ni àríyànjiyàn àti ìpèníjà ń gbérí — pàápàá jù lọ ti àṣe déédéé àti ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ ọlọ́pọ̀ ìtumọ̀.
Ọ̀rọ̀ àyálò nínú èdè Yorùbá: Bí èdè ṣe yí padà
Lílo àwọn ojúlówó ọ̀rọ̀ èdè Yorùbá pọ́nbélé máa ń mú kí àṣà — ó gbòòrò — tí yóò sí máa gbilẹ̀.
Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ ní Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn akẹgbẹ́-ẹ wọn láti sààmì ayẹyẹ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ọdún-un 2020
Àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀-ọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ orí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lágbàáyé láti sààmì Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé lọ́jọ́ 13 oṣù Èrèlé ọdún-un 2020 àti láti fọn rere iṣẹ́ ìdàgbàsókè àgbà-ńlá ayé tí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ń ṣe.