Ìròyìn nípa Nàìjíríà láti Ṣẹẹrẹ, 2023
‘Ìkòròdú bois’ ṣàfihàn bí àwọn gbàgede ẹ̀rọ-ayélujára ṣe ń ṣe ìgbélárugẹ àwọn eré àgbéléwò orílẹ̀-èdè Nàìjíríà káàkiri àgbáyé
Pẹ̀lú irinṣẹ́ tí kò tó àti àwọn àmúlò irinṣẹ́ orí ẹ̀rọ-ayárabíàṣá, ikọ̀ ‘Ìkòròdù Bois’ ṣe ìsínjẹ àti àwàdà àwọn eré Hollywood àti Nollywood tí ó ti di èrò yà wá á wò ó kárí ayé lórí àwọn gbàgede ìbáraẹnidọ́rẹ̀ẹ́.
Ìdílé Kútì tí ń fẹ̀hónúhàn nípasẹ̀ orin àti àwọn ọmọ Nigeria mìíràn tí wọ́n kọrin táko ẹlẹ́yàmẹ̀yà
Àwọn ìdílé Kútì ti gbógun ti àwọn adarí burúkú nípasẹ̀ orin. Bákan náà, àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nigeria bí Sonny Okosun, Majek Fashek àti Onyeka Onwenu jà láti rí i pé wọ́n dá Nelson Mandela sílẹ̀ ní ọgbà ẹ̀wọ̀n.
Orin ẹ̀hónú: àwọn ọ̀dọ́mọdé òǹkọrin ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ń kọrin tako ìwà ìrẹ́jẹ láwùjọ
Àwọn ọ̀dọ́mọdé olórin orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti tẹ̀síwájú nínú àṣà kíkọ orin tako ìrẹ́jẹ láwùjọ. Èhónú #EndSARS ṣe ìtanijí ọkàn wọn sí ìkópa nínú ètò òṣèlú, eléyìí tí ó ti ń wòòkùn.