Ìròyìn nípa Àṣà
Ìgbàgbọ́ ọba kan nínú ewé àtegbó fún ìwòsàn COVID-19 f'ara gbún ìmọ̀-ìjìnlẹ̀ l'órílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Ọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yìí nígbàgbọ́ nínú ewé àtegbó fún àwòtán COVID-19. Àmọ́ fífi Ògún gbárí láìfẹ̀rìílàdìí lórí Twitter fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbárìn lè ṣini lọ́kàn — ó sì léwu — fún àwọn ènìyàn.
Ọ̀rọ̀ àyálò nínú èdè Yorùbá: Bí èdè ṣe yí padà
Lílo àwọn ojúlówó ọ̀rọ̀ èdè Yorùbá pọ́nbélé máa ń mú kí àṣà — ó gbòòrò — tí yóò sí máa gbilẹ̀.
Olóyè yìí nírètí wí pé àwọn ọmọ Yorùbá yóò tẹ́wọ́ gba ‘alífábẹ́ẹ̀tì t'ó ń sọ̀rọ̀’ tí òun hu ìmọ̀ rẹ̀
Kíkọ Yorùbá nílànà Látíìnì yóò di àfìẹ́yìn láì pẹ́ nítorí ọmọ káàárọ̀-o-ò-jí-ire kan, Olóyè Tolúlàṣẹ Ògúntósìn, ti hùmọ̀ ìlànà ìṣọwọ́kọ tuntun fún kíkọ èdè Yorùbá
Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ ní Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn akẹgbẹ́-ẹ wọn láti sààmì ayẹyẹ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ọdún-un 2020
Àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀-ọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ orí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lágbàáyé láti sààmì Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé lọ́jọ́ 13 oṣù Èrèlé ọdún-un 2020 àti láti fọn rere iṣẹ́ ìdàgbàsókè àgbà-ńlá ayé tí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ń ṣe.
Ilẹ̀-Adúláwọ̀ rí àbọ̀ ẹgbẹẹgbẹ̀rún-lọ́nà-ẹgbẹ̀rún owóo dollar láti ọ̀dọ̀ Ilé-ìfowópamọ́sí ńláńlá fún ìgbéfúkẹ́ Iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá
“Nítorí àìtó ìdókoòwò ń'nú iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá àti àṣà, Ilẹ̀-Adúláwọ̀ kò sí ń'nú ọjà iṣẹ́ ọpọlọ, àti ìdáraáwò ní àgbáyé," Benedict Oramah, ààrẹ Afreximbank ló sọ bẹ́ẹ̀.
Ní Kenya àti Ethiopia, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ríran ‘àwòrán-ìtọ́nà’ àt'ọ̀run wá láti gbẹ́ ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀
Láti ayébáyé, ọ̀pọ̀ ènìyàn ló ti ní kò sí ẹ̀rí tí ó dájú wípé ìran àt'ọ̀run wá ni àwọn irú àlá báwọ̀nyí, tí wọn ń dẹ́jàá ìlera ọpọlọ irú ẹni bẹ́ẹ̀ tó pé òún ríran lójú àlá. Àmọ́ àwọn òjíṣẹ́ ẹ̀sìn Ìmàle, Júù àti Onígbàgbọ́ gbogboó ti jẹ́rìí sí ìran láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ent tí ó wá lójú àlá fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ọdún.
Ààmì ìdánimọ̀ orílẹ̀ èdèe Jamaica tí Kanye West lò di awuyewuye tí ó dá fìrìgbagbòó lórí ‘ìsààmì’
"Ìṣàkóso ìjọba tó lọ kò rí ọrọ̀ tó wà nínú àwọn ààmìi orílẹ̀ èdèe ‘Jamaica’ tàbí èyí [tó dúró fún] orílẹ̀ èdè bíi àsíá ìlú àti ti ológun..."
Ilé ẹ̀kọ́ ìmọ̀ orin kíkọ kan ṣoṣo ní Zanzibar ti fẹ́ di títì pa
For the 1,800 talented students who have trained at the DCMA, this is the only musical home they know, where they can learn and grow as professional musicians and artists.
Àyájọ́ Ọjọ́ Òmìnira ní Trinidad àti Tobago — àmọ́ ǹjẹ́ orílẹ̀-èdè náà ní òmìnira bí?
"Òmìnira yìí faramọ́ ẹni tí o jẹ́, ibi tí o ti ṣẹ̀ wá, ẹ̀jẹ̀ àti ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìwá tí ó wà nínú iṣan-ẹ̀jẹ̀ rẹ"
Àdàwólulẹ̀ ilé ayé-àtijọ́ ọlọ́dún-un 150 fi àìkáràmáìsìkí ìjọba sí àwọn ibi àjogúnbáa Bangladesh hàn
"Ọnà ara ilé náà kọjá àfẹnusọ tí a kò le è rí lára àwọn ilé mìíràn ní àwọn agbègbè àtijọ́ọ Dhaka. Fún ìdí èyí, [kò] yẹ kí ilé náà di àdàwólulẹ̀."