Ìjọba Tanzania fi Ajìjàgbara Ọmọ Orílẹ̀-èdèe Uganda sí àtìmọ́lé, wọ́n sì lé e kúrò nílùú

Dókítà Wairagala Wakabi [Àwòrán láti CIPESA tí a fi àṣẹ lò]

Wairagala Wakabi, àgbà ọ̀jẹ̀ ajàfẹ́tọ̀ọ́ ẹ̀rọ ayárabíàṣá tí ó wá láti Uganda, di ẹni àtìmọ́lé ní Pápákọ̀ òfuurufú Julius Nyerere International Airport ní Dar es Salaam, Tanzania lọ́jọ́ 25 oṣù Igbe.

A fi ìwé pe Wakabi kí ó wá á sọ̀rọ̀ níbi ètò Àyájọ́ Àwọn Olùgbèjà Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ní Tanzania ọlọ́dọọdún tí Àgbáríjọ Olùgbèjà Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Tanzania (THRDC) jẹ́ olùgbàlejò. Wakabi ni Olùdarí Àgbà Ìfọwọ́sowọ́pọ̀ Ètò-ìmúlò Ìmọ̀-ẹ̀rọ Gbogboògbò fún Ìlà-Oòrùn àti Gúúsù Ilẹ̀ Adúláwò (CIPESA), ọ̀kan gbòógì nínú ilé-iṣẹ́ tí ó ń ṣe ètò tí ó dá lórí ètò-ìmúlò ẹ̀rọ ayélujára àti òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ ní orí ayélujára ní ilẹ̀ Adúláwò.

Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ wákàtí tí a fi ọ̀rọ̀ wá Wakabi lẹ́nu wò, tí wọn kò sì jẹ́ kí ó rí agbẹjọ́rò, a dá a padà sí Uganda.

Àwọn aṣojú láti Àgbáríjọ Olùgbèjà Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn gbìyànjú láti jà fún un, àmọ́ a sọ fún wọn wípé fún “àǹfààní ìlú” ni a fi dá Wakabi padà sí ìlúu rẹ̀:

https://twitter.com/cipesaug/status/1121470855719129088?ref_src=twsrc%5Etfw

Bí ó ti lẹ̀ jẹ́ pé ìṣẹ̀lẹ̀ náà kò ju wákàtí díẹ̀ lọ, ó mú ìjáyà ńlá bá àwọn ajàfẹ́tọ̀ọ́ ní agbègbè náà, tí ọ̀ràn ìwà àìtọ́ tí orílẹ̀-èdèe Tanzania ń wù sí àwọn ajìjàgbara àti oníṣẹ́-ìròyìn ń peléke sí i. Nínú oṣù Belu ọdún tí ó ré kọjá, àwọn òṣìṣẹ́ Ìgbìmọ̀ tí ó ń Dáàbò bo Oníṣẹ́-ìròyìn, Angela Quintal àti Muthoki Mumo di ẹni àtìmọ́lé fún ọ̀pọ̀ wákàtí ní Dar es Salaam, Tanzania, tí ìwé ẹ̀rí ọmọ-ìlú-fún-ìrìnnàa wọ́n di gbígbà lọ́wọ́ọ wọn.

https://twitter.com/FelAnthonio/status/1121451586159554563?ref_src=twsrc%5Etfw

Human Rights Watch sọ wípé lábẹ́ ìṣàkóso ìjọba Ààrẹ John Magufuli Tanzania ti rí “ìrésílẹ̀ ìbọ̀wọ̀ fún òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ, ìkẹ́gbẹ́ àti àpéjọ dé ojú àmì”

Ní ọdún-un 2015, Orílẹ̀èdè Olómìnira Ìṣọ̀kan Tanzania kéde Ìgbésẹ̀ Ìrúfin Orí Ẹ̀rọ Ayélujára. Ní àárín ọdún kan tí a kéde òfin yẹn, ó ti tó bí ọmọ orílẹ̀ èdèe Tanzania 14 tí òfín ti mú tí a sì ti dálẹ́jọ́ lábẹ́ òfin fún pé wọ́n sọ̀rọ̀ mọ́ṣààsí sí ààrẹ lórí ẹ̀rọ alátagbà. Pẹ́pẹ́yẹ gbé ọmọ pọ̀n nínú oṣù Ẹrẹ́nà ọdún-un 2018 nígbàtí a gba Ìlànà Ẹ̀rọ Ayárabíàṣá (Ohun orí ayélujára) àti Ìtàkùrọ̀sọ Ìfìwéránṣẹ́ wọlé tí ó mú un ní túláàsì fún àwọn akọbúlọ́ọ̀gù láti fi orúkọ sílẹ̀ tí wọ́n á sì san owó orí tí ó tó bíi US $900 lọ́dún kí wọn ó tó lè gbé àtẹ̀jáde sí orí ayélujára. Èyí mú kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ búlọ́ọ̀gù aládàádúró ó wọ òkùnkùn.

Ìpalẹ́numọ́ iléeṣẹ́ akọ̀ròyìn aládàádúró  nípasẹ̀ àwọn àdàlù ìṣíwèé fún ilé iṣẹ́ akọ̀ròyìn àti ìrókẹ́kẹ́ mọ́ oníṣẹ́-ìròyìn ti di ìdẹ́rùbà, ìkóra-ẹni-ní-ìjánu àti ìbẹ̀rù láti sọ èrò ọkàn ẹni nípa àwọn olórí orílẹ̀ èdè náà.

Àtìmọ́lé àti ìdápadà Wakabi sí Uganda jẹ́  ìtẹ̀síwájú ìdojú-ìjà-kọ òmìnira ọ̀rọ̀ tòun èrò ọkàn ẹni ní Tanzania.

Bẹ̀rẹ̀ ìtàkùrọ̀sọ náà

Òǹkọ̀wé, jọ̀wọ́ àkọsílẹ̀ ìwọlé »

Ìlànà

  • Atukọ̀ yóò ṣ'àtúnwò gbogbo ìsọsí . Máà fi ìsọsíì rẹ sílẹ̀ ju ẹ̀rìnmejì lọ tàbí kí a kà á sí iṣẹ́-ìjẹ́-tí-a-o-fẹ́.
  • Jọ̀wọ́ fi ọ̀wọ̀ fún ẹlòmíràn . A ò ní fi àṣẹ sí ìsọsí ìkórìíra, ìṣekúṣe, àti ìdojú-ìjà-kọ ẹnikẹ́ni k.