Ìròyìn nípa Ìròyìn Ọmọ-ìlú
Orílẹ̀-Èdè Nàìjíríà fi òfin de ìrìn-àjò lójúnà ìṣàmójútó àwọn tó ti kó kòkòrò àìfojúrí COVID 19
Àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lórí ayélujára béèrè fún ìfòfindè arìnrìnàjò láti orílẹ̀-èdè tí COVID-19 ti gbilẹ̀. Èyí á ró ojúṣẹ́ orílẹ̀-èdè sí ìtànkálẹ̀ yìí lágbára.
Ìgbàgbọ́ ọba kan nínú ewé àtegbó fún ìwòsàn COVID-19 f'ara gbún ìmọ̀-ìjìnlẹ̀ l'órílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Ọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yìí nígbàgbọ́ nínú ewé àtegbó fún àwòtán COVID-19. Àmọ́ fífi Ògún gbárí láìfẹ̀rìílàdìí lórí Twitter fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbárìn lè ṣini lọ́kàn — ó sì léwu — fún àwọn ènìyàn.
Àwọn òṣìṣẹ́ iléeṣẹ́ aṣẹ̀wùtà orílẹ̀-èdè Cambodia daṣẹ́sílẹ̀ látàrí àìsan owó ọ̀yà wọn lásìkò àjàkálẹ̀ COVID-19
"A kò leè jẹ́ k'áwọn agbanisíṣẹ́ ó wí àwáwí tí yóò f'àfàsẹ́yìn fówó ọ̀yà àwọn òṣìṣẹ́, nítorí àwọn òṣìṣẹ́ ti jẹ gbèsè, wọn kò sì gbọdọ̀ jáfara láti san owó wọn."
Àwọn Iléèjọsìn ní Greece àti Àríwá Macedonia kọ̀ láti yí ọwọ́ àwọn ìlànà-ìsìn wọn padà k'ó ba má fàyè gba àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19 t'ó ń ràn ká
Ìlànà ìsìn tí a mọ̀ sí Jíjẹara àti mímu ẹ̀jẹ̀ Olúwa tàbí Oúnjẹ Ìkẹyìn ní èyí tí àwọn ọmọ lẹ́yìn Krístì tí ó ń tẹ̀lé ìlànà ìsìn àtijọ́ yóò máa pín wáìnì tí a ti sọ di mímọ́ mu pẹ̀lú ṣíbí kan náà, àwọn Ìjọ Àgùdàá máa ń jẹ ẹ̀bẹ àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí wọ́n fi ẹnu gbà lọ́wọ́ àlùfáà.
Sísọnù sínú ògbufọ̀: Ìdí tí Atúmọ̀ Google ṣe ń kùnà — nínú títúmọ̀ èdè Yorùbá — àti àwọn èdè mìíràn
Bí àwọn iléeṣẹ́ onímọ̀ ẹ̀rọ ṣe ń gbìyànjú láti mú kí ògbufọ̀ èdè wà lárọ̀ọ́wọ́tó fún onírúurú èdè lórí ayélujára, ni àríyànjiyàn àti ìpèníjà ń gbérí — pàápàá jù lọ ti àṣe déédéé àti ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ ọlọ́pọ̀ ìtumọ̀.
Ọ̀rọ̀ àyálò nínú èdè Yorùbá: Bí èdè ṣe yí padà
Lílo àwọn ojúlówó ọ̀rọ̀ èdè Yorùbá pọ́nbélé máa ń mú kí àṣà — ó gbòòrò — tí yóò sí máa gbilẹ̀.
Olóyè yìí nírètí wí pé àwọn ọmọ Yorùbá yóò tẹ́wọ́ gba ‘alífábẹ́ẹ̀tì t'ó ń sọ̀rọ̀’ tí òun hu ìmọ̀ rẹ̀
Kíkọ Yorùbá nílànà Látíìnì yóò di àfìẹ́yìn láì pẹ́ nítorí ọmọ káàárọ̀-o-ò-jí-ire kan, Olóyè Tolúlàṣẹ Ògúntósìn, ti hùmọ̀ ìlànà ìṣọwọ́kọ tuntun fún kíkọ èdè Yorùbá
Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ ní Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn akẹgbẹ́-ẹ wọn láti sààmì ayẹyẹ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ọdún-un 2020
Àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀-ọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ orí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lágbàáyé láti sààmì Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé lọ́jọ́ 13 oṣù Èrèlé ọdún-un 2020 àti láti fọn rere iṣẹ́ ìdàgbàsókè àgbà-ńlá ayé tí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ń ṣe.
Ilẹ̀-Adúláwọ̀ rí àbọ̀ ẹgbẹẹgbẹ̀rún-lọ́nà-ẹgbẹ̀rún owóo dollar láti ọ̀dọ̀ Ilé-ìfowópamọ́sí ńláńlá fún ìgbéfúkẹ́ Iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá
“Nítorí àìtó ìdókoòwò ń'nú iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá àti àṣà, Ilẹ̀-Adúláwọ̀ kò sí ń'nú ọjà iṣẹ́ ọpọlọ, àti ìdáraáwò ní àgbáyé," Benedict Oramah, ààrẹ Afreximbank ló sọ bẹ́ẹ̀.
Twitter di pápá ìròyìn ayédèrú lásìkò Ìdìbò ọdún-un 2019 ní Nàìjíríà
Twitter di pápá ayédèrú ìròyìn ìtako ẹ̀yà kan àti ìsọkiri ṣáájú ìdìbò, lásìkò ìdìbò àti lẹ́yìn ìdìbò ti ọdún-un 2019 lórílẹ̀-èdèe Nàìjíríà