
Àwòrán láti ọwọ́ Pete Linforth ní Pixabay. Ìlò àwòrán pẹ̀lú àṣẹ Pixabay, fún ìlò gbogboògbò.
Yẹ àkọsílẹ̀ àkànṣe Global Voices wò lórí ipa COVID-19 lágbàáyé.
Gẹ́gẹ́ bí àjò tí ó ń kápá ìtànkálẹ̀ àrùn ní Nàìjíríà ṣe sọ, àwọn èèyàn márùn-ún mìíràn ni wọ́n ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé wọ́n ti kó kòkòro àrùn COVID-19, àròpọ̀ iye àwọn tí wọ́n ní àrùn náà ní Nàìjíríà wá jẹ́ mẹ́jọ.
@Fmohnigeria has announced 5 new cases of #COVID19 in Nigeria bringing the total number confirmed cases in Nigeria to 8
All 5 cases had a travel history to the UK/USA
We urge Nigerians to remain calm as public health response activities are intensified across the country pic.twitter.com/yoKLHXoxhq
— NCDC (@NCDCgov) March 18, 2020
Iléeṣẹ́ Elétò Ìlera Orílẹ̀-èdè Nàìjírí @Fmohnigeria ti kéde àfikún ènìyàn 5 tí ó ti lùgbàdì #COVID19 ní Nàìjíríà èyí tí ó mú òǹkà àwọn tó ti kó àrùn náà di 8
Àwọn márààrún ló ti ṣe ìrìnàjò lọ sí UK/USA
A rọ àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kí wọ́n sinmẹ̀dọ̀ nítorí iṣẹ́ ìlera pàjáwìrì ń lọ ní mẹ̀lọmẹ̀lọ jákèjádò orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin Nàìjíríà pic.twitter.com/yoKLHXoxhq
— NCDC (@NCDCgov) Ọjọ́ 18, Oṣù Kẹta, ọdún 2020
Iye àwọn ẹni tí ó ní kòkòrò àrùn náà di mẹ́jọ ní ọjọ́ méjì lẹ́yìn tí dókítà E. Osagie Ehanire fìdí i rẹ múlẹ̀ ní ọjọ́ 16, oṣù Ẹrẹ́na pé wọ́n ti rí ẹni kẹ́ta tí ó kó kòkòrò àìfojúrí COVID-19, ìyen “ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kan tí ó lé ní ẹni ọgbọ̀n tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti United Kingdom ní ọjọ́ 13, oṣù Ẹrẹ́na.”
There is a 3rd confirmed case of #COVID19 in Nigeria.
The new case is a Nigerian National who recently returned from the UK, self-isolated & contacted @NCDCGov when she developed symptoms. She is clinically stable. Read the press release below: pic.twitter.com/RqV1QASayX
— Dr. E. Osagie Ehanire MD, FWACS (@DrEOEhanire) March 17, 2020
Ẹni kẹta ti lu gúdẹ kòkòrò àìfojúrí #COVID19 ní Nàìjíríà.
Ẹni náà ni ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ ti ìlú ọba UK dé, ó ṣe ìdánìkanwá tí ó sì kàn sí àjọ @NCDCGov nígbàttí ó rí àwọn àpẹẹrẹ àrùn náà. Ó gbọ́ ìtọ́jú. Ka àtẹ̀jáde ìròyìn nísàlẹ̀: pic.twitter.com/RqV1QASayX
— Dókítà. E. Osagie Ehanire MD, FWACS (@DrEOEhanire) Ọjọ́ 17, Oṣù Kẹta, ọdún 2020
Aláìsàn náà ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ fún ọjọ́ 14 ní ìlú Èkó, láàárín àsìkò yìí ni ó bẹ̀rẹ̀ sí i ní àmì àìsàn ibà àti ikọ̀. Aláìsàn náà wà ní ilé ìwòsàn tí wọ́n ti ń ṣètọ́jú Kòkòro àkóràn ní Yaba, ní Ìpínlẹ̀ Èkó. Ara rẹ̀ ti ń balẹ̀, ó sì ń dáhùn sí ìtọ́jú dáadáa.
Bí í iye àwọn ènìyàn tí ó kó kòkòrò àrùn COVID-19 ṣe ń pọ̀ sí i ni Nàìjíríà, ìjọba àpapọ̀ ti gbọ́ ohun tí àwọn aráàlú sọ ní ọjọ́ 18, oṣù Ẹrẹ́na nípa fífi òfin de àwọn tí ó ń rin ìrìn àjò láti orílẹ̀ èdè 13 bí i: China, Italy, Iran, South Korea, Spain, Japan, France, Germany, Norway, United States, United Kingdom, Netherlands àti Switzerland tí ó ní ju ènìyàn 1000 lọ tí ó ti kó kòkòrò àrùn Kòrónà láti má wọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Àwọn tí wọ́n ti wọ Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ láti àwọn orílẹ̀ èdè tí a dárúkọ yìí gbọ́dọ̀ ya ara wọn sọ́tọ̀ fún ọjọ́ 14.
Ọjọ́ 27 ni oṣù Èrèlé ní a fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé ọmọ orílẹ̀ èdè Italy kan tí ó rìn ìrìnàjò wá sí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ tí ó ní kòkòrò àrùn COVID-19.
Ẹni kejì tí a fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé ó ní kòkòrò àrùn yìí, gẹ́gẹ́ bí NCDC ṣe sọ jẹ́ ẹni tí ó rìnnà pàdé ẹni àkọ́kọ́ tí ó kó àrùn náà, tí ara rẹ̀ sì ti yá báyìí lẹ́yìn tí àyẹ̀wò méjì ti fi hàn pé àyẹ̀wò náà kò sí lára rẹ̀ mọ́. Ẹnìkejì yìí ò ní àrùn náà mọ́, wọ́n sì ti fi í sílẹ̀ kí ó máa lọ sílé ní ọjọ́ 13 oṣù Ẹrẹ́na, ọdún 2020,” gẹ́gẹ́ bíi àjọ NCDC ṣe sọ.
Àwọn Aráàlú lórí ayélujára béèrè fún Ìfòfin-de-Ìrìnàjò
Bí wọ́n ṣe ń bójú tó àrùn COVID-19 kò tẹ́ ọ̀pọ̀ aráàlú lórí ayélujára lọ́rùn, wón sì ti ń béèrè fún àwọn ìgbésẹ̀ tí ó lágbára láti dẹ́kun ìtànkálẹ̀ àrùn náà ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.
Ọmọ ìlú lórí ayélujára, Ayobami kéde pé ìgbésẹ̀ NCDC falẹ̀. Ó gbà wọ́n nímọ̀ràn pé “kí wọ́n dẹ́kun ṣíṣe àṣehàn lórí ayélujára kí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́!”
What we won’t do is to tell more lies, no one has attended to her since last night, she hasn’t been given medication and is not being treated! Stop the media parade and do some work! This isn’t about getting international accolades. https://t.co/OvpFgOa1mu
— Ayobami (@dondekojo) March 17, 2020
Ohun tí a ò fẹ́ ṣe ni irọ́ pípa, kò sí ẹni tó tọ́jú rẹ láti alẹ́ àná, kò lo oògùn bẹ́ẹ̀ kò gba ìwòsàn! Ẹ dẹ́kun ìpolongo nínú ìròyìn, kí ẹ múṣẹ́ ṣe! Ọ̀rọ̀ yìí kì í ṣe fún gbígba ìgbóríyìn láti ilẹ̀ òkèèrè. https://t.co/OvpFgOa1mu
— Ayobami (@dondekojo) Ọjọ́ 17, Oṣù Kẹta, ọdún 2020
Gideon sọ pé “ó yẹ kí ó bà wá lẹ́rù” pé ṣíṣe àyẹ̀wò fún kòkòrò àrùn COVID-19 ń falẹ̀ ní Nàìjíríà.
That the @dondekojo case has been confirmed as positive for Coronavirus should scare all of us. This person tried to get tested numerous times and was given the runaround by our healthcare providers and ministry of health. Had to shout on twitter before even testing.
— Gideon (@DondeonBeke) March 17, 2020
Ó yẹ kí ti @dondekojo tí a gbọ́ wí pé ó ti gbé jombo àrùn kòkòrò àìfojúrí kòrónà ó fi ìbẹ̀rù bojo sí wa lọ́kàn. Ẹni yìí gbìyànjú kí ó rí àyẹ̀wò ṣe lọ́pọ̀ ìgbà tí àwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera àti àjọ ètò ìlera sì ń dà á ríborìbo. Ó ké gbàjarè lórí twitter kí wọn ó tó ṣ'àyẹ̀wò fún un.
— Gideon (@DondeonBeke) Ọjọ́ 17, Oṣù Kẹta, oọdún 2020
“Ẹ fi òfin de àwọn arìnrìn-àjò tí ó fẹ́ wọlé láti àwọn orílẹ̀ èdè mìíràn” pàápàá jù lọ àwọn tí ó wá láti àwọn orílẹ̀ èdè tí àrùn náà ti gbilẹ̀, akọ̀ròyìn Bayo Olupohunda náà tẹnumọ:
Nobody is saying the FG should ban flights outrightly. We cannot ban Nigerians from coming into the country. But they must be quarantined & released once cleared of the virus. But you must restrict travellers coming in especially from countries affect by this virus. https://t.co/1QrUTyJ13O
— Bayo Olupohunda (@BayoOlupohunda) March 17, 2020
Kò s'ẹ́ni t'ó sọ wí pé kí ìjọba àpapọ̀ ó fi òfin de ìgbòkègbodò ọkọ̀ òfuurufú lẹ́ẹ̀kannáà. A kò leè gbẹ́sẹ̀ lé ìwọ̀lú àwọn ọmọ Nàìjíríà sínú orílẹ̀-èdè wọn. Àmọ́ wọ́n gbọdọ̀ ṣe ìṣémọ́lé kí wọn ó tó gba òmìnira lẹ́yìn tí ó bá hàn gbangbagbàngbà wí pé wọn kò ní kòkòrò àìfojúrí náà. Ṣùgbọ́n a ní láti kọ̀ ọ́ fún àwọn arìnrìn-àjò tí ó ń tí àwọn orílẹ̀-èdè tí kòkòrò àìfojúrí náà ń bá fínra wọlé. https://t.co/1QrUTyJ13O
— Bayo Olupohunda (@BayoOlupohunda) Ọjọ́ 17, Oṣù Ẹrẹ́nà odu2020
Dr. Whitewalker náà tẹnpẹlẹ mọ́ ọn pé kò sí ohun tí ó burú nínú fífi òfin de àwọn arìnrìn-àjò ní àkókò tí wọ́n ṣiṣẹ́ ìṣàdínkù ìtànkálẹ́ àrùn láti lè dẹ́kun àkóràn ní àsìkò ìtànkálẹ́ àrùn bí i irú èyí.
https://t.co/fk7mozscWn pic.twitter.com/KzADgQ6U5J
— WhiteHawk Dr (@MakweCatherine) March 17, 2020
Ìfòfin de ìrìnàjò fi àyè gba ìṣiṣẹ́ takuntakun láti gbógun ti àjàkálẹ̀ tí ó gba orílẹ̀-èdè kan.
— WhiteHawk Dr (@MakweCatherine) Ọjọ́ 17, Oṣù Ẹrẹ́nà ọdún 2020
Dr. Chikwe Ihekweazu, olórí àjọ NCDC, bẹ̀bẹ̀ pé àwọn ń “gbìyànjú GIDI láti rí i pé àwọn ṣe gbogbo ohun tí ó yẹ kí àwọn ṣe:
We’re extremely busy. Our call handlers are taking hundreds of calls every day, 24/7 including weekends, from across Nigeria
Please be patient with us & help us by pulling together. The criticism distracts us from critical work
We are trying VERY hard to meet all urgent needs
— Chikwe Ihekweazu (@Chikwe_I) March 17, 2020
Ojú wá dì fún iṣẹ́. Àwọn agbàpè wa ń gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpè lójoojúmọ́, láti àárọ̀ dalẹ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan títí kan ọjọ́ ìsinmi, jákèjádò Nàìjíríà.
Ẹ jọ̀wọ́ ẹ fi sùúrù sí i pẹ̀lú wa kí ẹ bá ṣiṣẹ́ papọ̀. Ìṣèdájọ́ ń fa ìfàsẹ́yìn fún iṣẹ́ tí ó pọn dandan tí ó yẹ kí a gbé ṣe.
À ń gbìyànjú láti dá gbogbo ènìyàn lóhùn ní mọ́sámọ́sá.
— Chikwe Ihekweazu (@Chikwe_I) March 17, 2020
Ní ọjọ́ 17 oṣù Ẹrẹ́na, ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ti kọ́kọ́ sọ pé kí wọ́n fi òfin de àwọn ọkọ̀ òfurufú tí ó ń bọ̀ láti àwọn orílẹ̀ èdè tí àrùn náà ti gbilẹ̀ bí i United Kingdom àti China, kí wọ́n tó dúró di ọjọ́ kejì kí wọ́n tó fi òfin náà múlẹ̀.
Cable Nigeria jábọ̀ gbogbo àwọn tí wọ́n wá láti àwọn orílẹ̀-èdè tí àrùn náà ti gbilẹ̀ ni wọ́n máa yà sọ́tọ̀ pẹ̀lú àbójútó fún ọjọ́ mẹ́rìnlá. Ìjọba àpapọ̀ sì fi òfin de fífún àwọn ènìyàn ní visa Nàìjíríà.
Ìfòfindèrìnàjò náà bẹ̀rẹ̀ ní àbámẹ́ta ọjọ́ 21, oṣù Ẹrẹ́nà, ọdún 2020, yóò sì wà fún ọ̀sẹ̣̀ mẹ́rin tí ó ṣe é ṣe kí wọ́n sún un síwájú lẹ́yìn àpérò.
Ọ̀pọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè ní ilẹ̀ Adúláwọ̀ ti ń gbé ìgbésẹ̀ láti ṣe àdínkù ìtànkálẹ̀ kòkòrò àrùn COVID-19. Lára àwọn ìgbésẹ̀ yìí ni fífi òfin de ìrìn-àjò láti àwọn orílẹ̀ èdè tí kòkòrò àrùn COVID-19 náà ti gbilẹ̀ láti má ṣe wọ orílẹ̀ èdè wọn.
Ìṣàmójútó tí kò péye tó
Àwọn ìjábọ̀ kan wà nípa bí ìṣàmójútó àwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera kò ṣe péye tó lórí àwọn tó ní kòkòrò àrùn COVID-19 ni orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Obìnrin kan tí ó jẹ́ ẹni ọdún 70 tí ó ti lo oṣù márùn-ún ní United Kingdom padà sí Nàìjíríà ní ọjọ́ 11 oṣù Ẹrẹ́na. Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ tí ó dé, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní àmì àìsàn kòkòrò àrùn COVID-19 bí i òtútù àti ikun tí ó pọ̀ lápọ̀jù ní ọjọ́ 13, oṣù Ẹrẹ́na. Wọ́n sì sáré gbé lọ sí Teaching Hospital ti ìpínlẹ̀ Enugu (ESUTH) Colliery Parklane, ní gúúsù ìlà-oòrùn Nàìjíríà.
Wọ́n yà á sọ́tọ̀ ní ESUTH Colliery Parklane, wọ́n sì fi àyẹ̀wọ̀ tí wọ́n ṣe fun un ṣọwọ́ sí àjọ NCDC ní ọjọ́ 14, oṣù Ẹrẹ́na fún àyẹ̀wò. Ní ọjọ́ 15, oṣù Ẹrẹ́na, obìnrin náà kú lẹ́yìn tí àjọ NCDC jábọ̀ pé kò ní kòkòrò àrùn COVID-19.
The laboratory result of the patient in Enugu suspected to have #COVID19 is NEGATIVE
It is important to wait for confirmation from NCDC before spreading information on social media.
NCDC will continue to provide updates to the publichttps://t.co/zQrpNeOfet https://t.co/chldqET4Wz pic.twitter.com/SLS4Dw8Zyk
— NCDC (@NCDCgov) March 15, 2020
Èsì àyẹ̀wò aláìsàn ní Ìpínlẹ̀ Enugu tó jẹ́ ìfurasí pé #COVID19 ni kò rí bẹ́ẹ̀.
Ó ṣe kókó kí a tẹ̀lé ìfẹsẹ̀múlẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àjọ̀ NCDC kí a tó máa pín ìwífún lórí ẹ̀rọ agbọ́rọ̀káyé. .
NCDC yóò túbọ̀ máa taari àwọn àbájáde síta fún t'onílé t'ẹlẹ́mù https://t.co/zQrpNeOfet https://t.co/chldqET4Wz pic.twitter.com/SLS4Dw8Zyk
— NCDC (@NCDCgov) Ọjọ́ 15, Oṣù Ẹrẹ́nà, ọdún 2020
Bẹ́ẹ̀, nínú lẹ́tà tí wọ́n kọ sí gómìnà ìpínlẹ̀ Enugu, ọmọ obìnrin náà fẹ̀sùn kan àwọn òṣìṣẹ́ ilé ìwòsàn náà pé “tàbùkù” ìyá òun, wọ́n gbé e sínú “ilé àkọ́kù” tí ó kún fún koríko.
Ọ̀rọ̀ ẹnìkan tí ó ní kòkòrò àrùn COVID-19 tí wọn kò ṣe àbójútó tó péye fún wáyé ní ìpínlẹ̀ Èkó tí ó jẹ́ olú-ìlú ìdókòòwò ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Ní ọjọ́ 17, oṣù Ẹrẹ́na, David Hundeyin tí ó jẹ́ akọ̀ròyìn pẹ̀lú News Wire, jábọ̀ nípa ìṣàmójútó tí kò gúnrégé tó lórí ọ̀rọ̀ ẹni tí wọ́n furasí pé ó ní kòkòrò àrùn COVID-19 ní ilé iṣẹ́ Dangote ní Ibeju-Lekki, ní Ìpínlẹ̀ Èkó, tí ó sì ti ń fa ìpayà láàárín àwọn òṣìṣẹ́ ibẹ̀.
Ní ọjọ́ kejìlá oṣù Ẹrẹ́nà, òṣìṣẹ́ iléeṣẹ́ Dangote kan tí ó jẹ́ ọmọ ilẹ̀ India tí ó ń tún ọ̀pá omi ṣe wá sí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti Mumbai, lẹ́yìn tí ó dúró díẹ̀ ní Cairo, ní orílẹ̀-èdè Egypt. Ìwádìí Hudeyin fi hàn pé ọkùnrin náà tí ó ń tún ọ̀pá omi ṣe bẹ̀rẹ̀ sí i ní “ibà, ikọ́ gbígbẹ, ọ̀fun dídùn àti àìlè mí délẹ̀,” ní ọjọ́ kejì tí ó dé láti India. Síbẹ̀, “kò tí ì hàn bóyá ẹnikẹ́ni ní iléeṣẹ́ Dangote ti gbìyànjú láti kàn sí” àwọn elétò ìlera tí ọ̀rọ̀ náà kàn.
Hudeyin sọ̀rọ̀ síwájú pé ilé iṣẹ́ náà ń lo àǹfààní “àyíká òfin tí kò múnádóko tó” ní Nàìjíríà “láti fi èrè tirẹ̀ síwájú”, èyí sì ń fi ẹ̀mí àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àwùjọ sínú ewu.
Ìròyìn yìí mú kí iléeṣẹ́ náà gbé èrò wọn jáde pé àwọn ti gbé aláìsàn náà lọ sí ilé ìwòsàn tí wọ́n ti ń ṣètọ́jú kòkòrò Àkóràn ní Yaba, ní ìpínlẹ̀ Èkó.